Ilé-iṣẹ́ ìfọpo bentiró Dangote kò fi dọ́là ta epo si àwọn ọjà Nigeria

Share

Àwòránhùn ètò àgbésáfẹ́fẹ́ kan láti ọwọ́ News Central TV tí ń tàn káàkiri orí ẹ̀rọ-ayélujára pẹ̀lú àhesọ pé ilé-iṣẹ́ ìfọpo Dangote sọ pé òun yóò máa ta epo ọkọ̀ (PMS) a mọ̀ sí ‘epobẹntirólábẹ́lé si àwọn ọjà Nigeria ní owó dọ́là.

Àwòránhùn náà, @instablog9ja gbé jade lórí ìkànnì X, pẹ̀lú àhesọ náà ti tàn káàkiri bẹ́ẹ̀ sì ni àwọn aṣàmúlò X mìíràn ti pín in.

ÀBÁJÁDE ÌWÁDÌÍ WA: ÌSINILỌ́NÀ NÍ ÀHESỌ YÌÍ

Àwọn ìwádìí láti ọwọ́ ilé-iṣẹ́ FactCheckHub fi hàn pé àwòrán tí ó ń tàn náà ni News Central TV fi sórí ẹ̀rọ ayélujára j 26, Oṣù Kẹ̀sán-án, dun 2023, atipe ṣẹ̀ṣẹ̀ níta.

Nígbà tí ó ń fèsì sí àhesọ náà, Ukadike Chinedu, agbenusọ fúnàwọn Independent Petroleum Marketers Association of Nigeria (IPMAN) nínú ìròyìn kan tí wọ́n gbé jáde ninu ìwéìròyìn Punch kan òṣù kìíní, ọdun 2024 tako àhesọ náà.

Owó òfin mọ̀ ní Nigeria ni náírà. Náírà ni símẹ́ńtì tí Dangote ń tà, kì í ṣe dọ́là. Sìpàgẹ́tì àti àwọn ọjà pàtàkì mìíràn tí ó ń tà náírà ni ó ń tà wọ́n pẹ̀lú. Nítorí náà, kín ló dé tí èèyàn yóò ronú pé yóò ta epo bentiró ní dọ́là?,” Chinedu sọ èyí.

Nígbà a n i, Anthony Chiejina, agbenusọ fun ilé-iṣẹ́ Dangote Group, ṣe àpèjúwe àwòránhùn náà pẹ̀lú àhesọ tí ó ń tàn ká bí “ìròyìn ayédèrú”.

Most Read

Recent Checks